Saamu 115:1-18 OYCB

[1] Kì í ṣe fún wa, OLÚWA kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ. [2] Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà. [3] Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú. [4] Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni. [5] Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran. [6] Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn. [7] Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn. [8] Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn. [9] Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn [10] Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn. [11] Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù OLÚWA, gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn. [12] OLÚWA tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni. [13] Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù OLÚWA, àti kékeré àti ńlá. [14] OLÚWA yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀. [15] Ẹ fi ìbùkún fún OLÚWA ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé. [16] Ọ̀run àní ọ̀run ni ti OLÚWA: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn. [17] Òkú kò lè yìn OLÚWA, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. [18] Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún OLÚWA láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin OLÚWA.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.