Saamu 114:1-8 OYCB

[1] Nígbà tí Israẹli jáde ní Ejibiti, ilé Jakọbu láti inú ènìyàn àjèjì èdè [2] Juda wà ní ibi mímọ́, Israẹli wà ní ìjọba. [3] Òkun sì rí i, ó sì wárìrì: Jordani sì padà sẹ́yìn. [4] Àwọn òkè ńlá ń fò bí àgbò àti òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn. [5] Kí ni ó ṣe ọ́, ìwọ Òkun, tí ìwọ fi wárìrì? Ìwọ Jordani, tí ìwọ fi padà sẹ́yìn? [6] Ẹ̀yin òkè ńlá kí ló dé ti ẹ fi ń fò bí àgbò, àti ẹ̀yin òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn? [7] Wárìrì, ìwọ ilẹ̀, níwájú OLÚWA; ní iwájú Ọlọ́run Jakọbu [8] tí ó sọ àpáta di adágún omi, àti òkúta-ìbọn di orísun omi.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.