Saamu 116:1-19 OYCB

[1] Èmi fẹ́ràn OLÚWA, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú. [2] Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè. [3] Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. [4] Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ OLÚWA: “OLÚWA, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!” [5] OLÚWA ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú. [6] OLÚWA pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí. [7] Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí OLÚWA ṣe dáradára sí ọ. [8] Nítorí ìwọ, OLÚWA, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú, [9] nítorí èmi yóò máa rìn níwájú OLÚWA ní ilẹ̀ alààyè. [10] Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”. [11] Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”. [12] Kí ni èmi yóò san fún OLÚWA nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi? [13] Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ OLÚWA. [14] Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí OLÚWA ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀. [15] Iyebíye ní ojú OLÚWA àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀. [16] OLÚWA, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi. [17] Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ OLÚWA. [18] Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí OLÚWA ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀, [19] nínú àgbàlá ilé OLÚWA ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin OLÚWA.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.