Saamu 113:1-9 OYCB

[1] Ẹ máa yin OLÚWA. Yìn ín ẹ̀yin ìránṣẹ́ OLÚWA, ẹ yin orúkọ OLÚWA. [2] Fi ìbùkún fún orúkọ OLÚWA láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. [3] Láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀ orúkọ OLÚWA ni kí a máa yìn. [4] OLÚWA ga lórí gbogbo orílẹ̀-èdè, àti ògo rẹ̀ lórí àwọn ọ̀run. [5] Ta ló dàbí OLÚWA Ọlọ́run wa, tí ó gbé ní ibi gíga. [6] Tí ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ láti wò òun tí ó ń bẹ lọ́run, àti nínú ayé! [7] Ó gbé òtòṣì dìde láti inú erùpẹ̀, àti pé ó gbé aláìní sókè láti inú ààtàn wá. [8] Kí ó le mú un jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé àní pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé àwọn ènìyàn rẹ̀. [9] Ó mú àgàn obìnrin gbé inú ilé, àti láti jẹ́ aláyọ̀ ìyá fún àwọn ọmọ rẹ̀. Ẹ yin OLÚWA.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.