Saamu 93:1-5 OYCB

[1] OLÚWA ń jẹ ọba, ọláńlá ni ó wọ̀ ní aṣọ; ọláńlá ni OLÚWA wọ̀ ní aṣọ àti ìhámọ́ra rẹ̀ pẹ̀lú agbára. Ó fi ìdí ayé múlẹ̀; kò sì le è yí. [2] Ìjọba rẹ̀ wà láti ọjọ́ pípẹ́; ìwọ wà títí ayérayé. [3] A ti gbé òkun sókè, OLÚWA, òkun ti gbé ohùn wọn sókè; òkun ti gbé rírú omi wọn sókè. [4] Ó ni ògo ju àrá omi ńlá lọ, ó ni ògo ju òkun rírú lọ OLÚWA ga ní ògo. [5] Ẹ̀rí rẹ̀ dúró ṣinṣin; ìwà mímọ́ ni ó fi ṣe ilé rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ fún ọjọ́ àìlópin, OLÚWA.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.