[1] Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún OLÚWA àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo, [2] láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́, [3] lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu. [4] Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ OLÚWA; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ. [5] Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, OLÚWA? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni! [6] Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n, [7] nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé. [8] Ṣùgbọ́n ìwọ OLÚWA ni a ó gbéga títí láé. [9] Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, OLÚWA, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká. [10] Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí. [11] Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi. [12] Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni, [13] tí a gbìn sí ilé OLÚWA, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa. [14] Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini, [15] láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni OLÚWA; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”