Saamu 30:1-12 OYCB

[1] Èmi yóò kókìkí i rẹ, OLÚWA, nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí. [2] OLÚWA Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, ìwọ sì ti wò mí sàn. [3] OLÚWA, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú, mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò. [4] Kọ orin ìyìn sí OLÚWA, ẹ̀yin olódodo; kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́. [5] Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀, ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé; ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́, ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀. [6] Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé, “a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.” [7] Nípa ojúrere rẹ, OLÚWA, ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára; ìwọ pa ojú rẹ mọ́, àyà sì fò mí. [8] Sí ọ OLÚWA, ni mo ké pè é; àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú: [9] “Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi, nínú lílọ sí ihò mi? Eruku yóò a yìn ọ́ bí? Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ? [10] Gbọ́, OLÚWA, kí o sì ṣàánú fún mi; ìwọ OLÚWA, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.” [11] Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi; ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí, [12] nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́. Ìwọ OLÚWA Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.