Saamu 29:1-11 OYCB

[1] Ẹ fi fún OLÚWA, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún OLÚWA, ògo àti alágbára. [2] Fi fún OLÚWA, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin OLÚWA nínú ẹwà ìwà mímọ́. [3] Ohùn OLÚWA n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, OLÚWA san ara. [4] Ohùn OLÚWA ní agbára; ohùn OLÚWA kún fún ọláńlá. [5] Ohùn OLÚWA fa igi kedari; OLÚWA náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya. [6] Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré. [7] Ohùn OLÚWA ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà. [8] Ohùn OLÚWA ń mi aginjù. OLÚWA mi aginjù Kadeṣi. [9] Ohùn OLÚWA ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!” [10] OLÚWA jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; OLÚWA jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé. [11] Kí OLÚWA fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.