Saamu 98:1-9 OYCB

[1] Ẹ kọrin tuntun sí OLÚWA, nítorí tí ó ṣe ohun ìyanu; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti apá mímọ́ rẹ̀ o ṣe iṣẹ́ ìgbàlà fún un [2] OLÚWA ti sọ ìgbàlà rẹ̀ di mí mọ̀ o fi òdodo rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè. [3] Ó rántí ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ fún àwọn ará ilé Israẹli; gbogbo òpin ayé ni ó ti rí iṣẹ́ ìgbàlà Ọlọ́run wa. [4] Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí OLÚWA, gbogbo ayé, ẹ bú sáyọ̀, ẹ kọrin ìyìn, [5] ẹ fi dùùrù kọrin sí OLÚWA, pẹ̀lú dùùrù àti ìró ohùn orin mímọ́, [6] pẹ̀lú ìpè àti fèrè ẹ hó fún ayọ̀ níwájú OLÚWA ọba. [7] Jẹ́ kí òkun kí ó hó pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀, Gbogbo ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀. [8] Ẹ jẹ́ kí odo kí ó ṣápẹ́, ẹ jẹ́ kí òkè kí ó kọrin pẹ̀lú ayọ̀; [9] ẹ jẹ́ kí wọn kọrin níwájú OLÚWA, nítorí tí yóò wá ṣèdájọ́ ayé bẹ́ẹ̀ ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè nínú òdodo àti àwọn ènìyàn ní àìṣègbè pẹ̀lú.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.