Saamu 33:1-22 OYCB

[1] Ẹ yọ̀ nínú OLÚWA, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin. [2] Ẹ yin OLÚWA pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i. [3] Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo. [4] Nítorí pé ọ̀rọ̀ OLÚWA dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́. [5] Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú OLÚWA. [6] Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ OLÚWA ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀. [7] Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo. [8] Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù OLÚWA: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀. [9] Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin. [10] OLÚWA ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í. [11] Ìgbìmọ̀ OLÚWA dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni. [12] Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí OLÚWA jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀. [13] OLÚWA wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn. [14] Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé [15] ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn. [16] A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀. [17] Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀. [18] Wò ó, ojú OLÚWA wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin. [19] Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn. [20] Ọkàn wa dúró de OLÚWA; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa. [21] Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́. [22] Kí àánú rẹ, OLÚWA, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.