Saamu 3:1-8 OYCB

[1] OLÚWA, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí! Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó! [2] Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé “Ọlọ́run kò nígbà á là.” Sela. [3] Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, OLÚWA; ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè. [4] OLÚWA ni mo kígbe sókè sí, ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. Sela. [5] Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn; mo sì tún padà jí, nítorí OLÚWA ni ó ń gbé mi ró. [6] Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká. [7] Dìde, OLÚWA! Gbà mí, Ọlọ́run mi! Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n; kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú. [8] Láti ọ̀dọ̀ OLÚWA ni ìgbàlà ti wá. Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. Sela.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.