Saamu 150:1-6 OYCB

[1] Ẹ fi ìyìn fún OLÚWA. Ẹ fi ìyìn fún Ọlọ́run ní ibi mímọ́ rẹ̀, ẹ yìn ín nínú agbára ọ̀run rẹ̀. [2] Ẹ yìn ín fún iṣẹ́ agbára rẹ̀. Ẹ yìn ín fún títóbi rẹ̀ tí ó tayọ̀. [3] Ẹ fi ohùn ìpè yìn ín. Ẹ fi ohun èlò orin yìn ín. [4] Ẹ fi ohun èlò orin àti ijó yìn ín fi ohun èlò orin olókùn àti ìpè yìn ín, [5] Ẹ yìn ín pẹ̀lú aro olóhùn òkè, ẹ yìn ín lára aro olóhùn gooro. [6] Jẹ́ kí gbogbo ohun tí ó ní ẹ̀mí yin OLÚWA. Ẹ fi ìyìn fún OLÚWA.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.