Saamu 135:1-21 OYCB

[1] Ẹ yin OLÚWA. Ẹ yin orúkọ OLÚWA; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ OLÚWA. [2] Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé OLÚWA, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa. [3] Ẹ yin OLÚWA: nítorí tí OLÚWA ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn. [4] Nítorí tí OLÚWA ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀. [5] Nítorí tí èmi mọ̀ pé OLÚWA tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ. [6] OLÚWA ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo. [7] Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá. [8] Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko. [9] Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo. [10] Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba. [11] Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani: [12] Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀. [13] OLÚWA orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ OLÚWA, láti ìrandíran. [14] Nítorí tí OLÚWA yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. [15] Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni. [16] Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran. [17] Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn. [18] Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn. [19] Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún OLÚWA, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún OLÚWA. [20] Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún OLÚWA; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù OLÚWA, fi ìbùkún fún OLÚWA. [21] Olùbùkún ni OLÚWA, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún OLÚWA.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.