Saamu 130:1-8 OYCB

[1] Láti inú ibú wá ni èmi ń ké pè é ọ́ OLÚWA [2] OLÚWA, gbóhùn mi, jẹ́ kí etí rẹ kí o tẹ́ sílẹ̀ sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi. [3] OLÚWA, ìbá ṣe pé kí ìwọ máa sàmì ẹ̀ṣẹ̀, OLÚWA, tá ni ìbá dúró. [4] Nítorí ìdáríjì wà lọ́dọ̀ rẹ, kí a lè máa bẹ̀rù rẹ. [5] Èmi dúró de OLÚWA, ọkàn mi dúró, àti nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni èmi ń ṣe ìrètí. [6] Ọkàn mi dúró de OLÚWA, ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ, àní ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ. [7] Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti OLÚWA: nítorí pé lọ́dọ̀ OLÚWA ni àánú wà, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdáǹdè wà. [8] Òun ó sì dá Israẹli ní ìdè kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ gbogbo.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.