Saamu 126:1-6 OYCB

[1] Nígbà tí OLÚWA mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá. [2] Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, OLÚWA ṣe ohun ńlá fún wọn. [3] OLÚWA ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀. [4] OLÚWA mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù. [5] Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka. [6] Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.