Saamu 124:1-8 OYCB

[1] “Ìbá má ṣe pé OLÚWA tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí; [2] ìbá má ṣe pé OLÚWA tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa, [3] nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa, [4] nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀, [5] nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa. [6] Olùbùkún ni OLÚWA, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn. [7] Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ. [8] Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ OLÚWA, tí ó dá ọ̀run òun ayé.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.