Saamu 121:1-8 OYCB

[1] Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì—níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá? [2] Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ OLÚWA wá, ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé. [3] Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀; ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé. [4] Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́, kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn. [5] OLÚWA ni olùpamọ́ rẹ; OLÚWA ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ. [6] Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán tàbí òṣùpá ní ìgbà òru. [7] OLÚWA yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo yóò pa ọkàn rẹ mọ́ [8] OLÚWA yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́ láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.