[1] Ẹ fi ọpẹ́ fún OLÚWA, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé. [2] Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”. [3] Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”. [4] Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù OLÚWA wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.” [5] Nínú ìrora mi, mo sọkún sí OLÚWA, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀. [6] OLÚWA ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi? [7] OLÚWA ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi. [8] Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ. [9] Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ. [10] Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ OLÚWA èmi gé wọn kúrò. [11] Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ OLÚWA èmi gé wọn dànù. [12] Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ OLÚWA èmi ké wọn dànù. [13] Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n OLÚWA ràn mí lọ́wọ́. [14] OLÚWA ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi. [15] Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún OLÚWA ń ṣe ohun agbára! [16] Ọwọ́ ọ̀tún OLÚWA ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún OLÚWA ń ṣe ohun agbára!” [17] Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí OLÚWA ṣe. [18] OLÚWA bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́. [19] Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún OLÚWA. [20] Èyí ni ìlẹ̀kùn OLÚWA ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé. [21] Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi. [22] Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé; [23] OLÚWA ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa. [24] Èyí ni ọjọ́ tí OLÚWA dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀. [25] OLÚWA, gbà wá; OLÚWA, fún wa ní àlàáfíà. [26] Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ OLÚWA. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé OLÚWA wá. [27] OLÚWA ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ. [28] Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga. [29] Ẹ fi ọpẹ́ fún OLÚWA, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.