Saamu 100:1-5 OYCB

[1] Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí OLÚWA, gbogbo ayé. [2] Ẹ fi ayọ̀ sin OLÚWA, ẹ wá síwájú rẹ̀ pẹ̀lú orin dídùn [3] OLÚWA Ọlọ́run ni ó dá wa, kí ẹ̀yin kí ó mọ̀ pé tirẹ̀ ni àwa, àwa ní ènìyàn rẹ̀ àti àgùntàn pápá rẹ̀. [4] Ẹ lọ sí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ àti sí àgbàlá rẹ̀ pẹ̀lú ìyìn; ẹ fi ọpẹ́ àti ìyìn fún orúkọ rẹ̀. [5] Nítorí tí OLÚWA pọ̀ ní oore ìfẹ́ rẹ̀ sì wà títí láé; àti òtítọ́ rẹ̀ láti ìran de ìran.

About this translation

Life Bible app icon
Get the Life Bible app Read offline, sync highlights and notes, and study with your library on any device.