Numeri 33:1-56 OYCB
[1] Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni. [2] Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ OLÚWA, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn. [3] Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti. [4] Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí OLÚWA ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí OLÚWA ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn. [5] Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti. [6] Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù. [7] Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli. [8] Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara. [9] Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀. [10] Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa. [11] Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini. [12] Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka. [13] Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi. [14] Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu. [15] Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai. [16] Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa. [17] Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu. [18] Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma. [19] Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi. [20] Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina. [21] Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa. [22] Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata. [23] Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi. [24] Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada. [25] Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu. [26] Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati. [27] Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra. [28] Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka. [29] Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona. [30] Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu. [31] Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani. [32] Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi. [33] Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata. [34] Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona. [35] Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi. [36] Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini. [37] Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu. [38] Nípa àṣẹ OLÚWA, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá. [39] Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta (123) ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori. [40] Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀. [41] Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona. [42] Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni. [43] Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu. [44] Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu. [45] Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi. [46] Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu. [47] Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo. [48] Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko. [49] Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu. [50] Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, OLÚWA sọ fún Mose pé, [51] “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani, [52] lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀. [53] Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín. [54] Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn. [55] “ ‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé. [56] Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’ ”
